Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 46:20-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Ní Éjíbiti, Áṣénátù ọmọbìnrin Pọ́tíférà, alábojútó àti àlùfáà Ónì, bí Mánásè àti Éfúráímù fún Jósẹ́fù.

21. Àwọn ọmọ Bẹ́ńjámínì:Bélà, Békérì, Áṣíbélì, Gérà, Náámánì, Éhì, Rósì, Múpímù, Húpímù àti Árídà.

22. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rákẹ́lì bí fún Jákọ́bù. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá (14) lápapọ̀.

23. Àwọn ọmọ Dánì:Úsímù.

24. Àwọn ọmọ Náfítalì:Jáháṣíè, Gúnì, Jésérì, àti Ṣílémù.

25. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Bílíhà ẹni tí Lábánì fi fún Rákélì ọmọ rẹ̀ bí fún Jákọ́bù. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.

26. Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jákọ́bù sí Éjíbítì, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láì ka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìndín-ní-àadọ́rin (66).

27. Pẹ̀lú àwọn ọmọkùnrin méjì tí a bí fún Jósẹ́fù ní Éjíbítì àwọn ará ilé Jákọ́bù tí ó lọ sí Éjíbítì jẹ́ àádọ́rin (70) lápapọ̀

28. Jákọ́bù sì rán Júdà ṣáájú rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Jósẹ́fù, kí wọn báà le mọ ọ̀nà Gósénì. Nígbà tí wọ́n dé agbégbé Gósénì,

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 46