Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 45:21-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì ṣe èyí. Jósẹ́fù fún wọn ni kẹ̀kẹ́ ẹrù bí Fáráò ti pàṣẹ, ó sì fún wọn ní oúnjẹ fún ìrìn-àjò wọn pẹ́lú.

22. Ó fún ẹni kọ̀ọ̀kan wọn ní aṣọ tuntun. Ṣùgbọ́n Bẹ́ńjámínì ni ó fún ní ọ̀ọ́dúnrún ẹyọ owó (300) idẹ fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ márùn ún.

23. Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó kó ránṣẹ́ sí baba rẹ̀: kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá tí ó ru àwọn ohun mèremère ilẹ̀ Éjíbítì àti abo kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ mẹ́wàá tí ó ru ọkà àti oríṣìíríṣìí oúnjẹ.

24. Nígbà náà ni ó rán àwọn arákùnrin rẹ̀ lọ, bí wọ́n ṣe ń pínyà, ó wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe jà ní ọ̀nà o!”

25. Báyìí ni wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Éjíbítì wá sí ọ̀dọ̀ Jákọ́bù baba wọn ní ilẹ̀ Kénánì.

26. Wọn wí fún un pé, “Jósẹ́fù sì wà láàyè! Kódà òun ni alákòóṣo ilẹ̀ Éjíbítì” Ẹnu ya Jákọ́bù, kò sì gbà wọ́n gbọ́

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 45