Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 43:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Báyìí, ìyàn náà sì mú gidigidi ní ilẹ̀ náà.

2. Nígbà tí wọ́n sì ti jẹ gbogbo ọkà tí wọ́n rà ní Éjíbítì tan, baba wọn wí fún wọn pé, “Ẹ padà lọ ra oúnjẹ́ díẹ̀ si wá fún wa.”

3. Ṣùgbọ́n Júdà wí fún un pé, “Ọkùnrin náà tẹnumọ́ ọn nínú ìkìlọ̀ rẹ̀ fún wa pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò rí ojúrere mi mọ́, àyàfi bí arákùnrin yín bá bá a yín wá’.

4. Tí ìwọ yóò bá rán Bẹ́ńjámínì arákùnrin wa lọ pẹ̀lú wa, a ó lọ ra oúnjẹ wá fún ọ.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 43