Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 41:53-57 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

53. Ọdún méje ọ̀pọ̀ oúnjẹ sì wá sí òpin ní ilẹ̀ Éjíbítì,

54. Ọdún méje ìyàn sì bẹ̀rẹ̀, bí Jósẹ́fù ti wí gan-an. Ìyàn sì mú ní gbogbo ilẹ̀ tó kù, ṣùgbọ́n oúnjẹ wà ní gbogbo ilẹ̀ Éjíbítì.

55. Nígbà tí àwọn ará Éjíbítì bẹ̀rẹ̀ sí ní rí ipá ìyàn náà, wọ́n kígbe sí Fáráò. Nígbà náà ni Fáráò wí fún wọn pé, “Ẹ lọ bá Jóṣẹ́fù, ẹ ṣe ohun tí ó bá wí fún un yín.”

56. Nígbà tí ìyàn sì ti tàn ká gbogbo ilẹ̀ náà, Jósẹ́fù sí inú àká, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ta ọkà fún àwọn ènìyàn, nítorí ìyàn náà mú gan-an ní gbogbo ilẹ̀ Éjíbítì.

57. Gbogbo àwọn orílẹ̀ èdè sì ń wá láti ra oúnjẹ lọ́wọ́ Jósẹ́fù, nítorí ìyàn náà pọ̀ gidigidi káàkiri gbogbo ayé.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 41