Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 4:3-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Káínì mú ọrẹ wá fún Olúwa nínú èṣo ilẹ̀ rẹ̀.

4. Ṣùgbọ́n Ábélì mú ẹran tí ó sanra wá fún Olúwa nínú àkọ́bí ẹran-ọ̀sìn rẹ̀. Olúwa sì fi ojú rere wo Ábélì àti ọrẹ rẹ̀,

5. ṣùgbọ́n Olúwa kò fi ojú rere wo Káínì àti ẹbọ rẹ̀. Nítorí náà inú bí Káínì gidigidi, ojú rẹ̀ sì fàro.

6. Nígbà náà ni Olúwa bi Káínì pé, “Èéṣe tí ìwọ ń bínú? Èéṣe tí ojú rẹ sì fàro?

7. Bí ìwọ ba ṣe ohun tí ó tọ́, ṣé ìwọ kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà? Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ṣe ohun tí ó tọ́, ẹ̀ṣẹ̀ ń bẹ ní ẹnu ọ̀nà rẹ, ó fẹ́ ní ọ ní ìní, ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ ṣe àkóso rẹ̀.”

8. Káínì wí fún Ábélì arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ kí a lọ sí oko.” Ó sì ṣe, bí wọ́n ti wà ní oko; Káínì da ojú ìjà kọ Ábélì arákùnrin rẹ̀, ó sì pa á.

9. Nígbà náà ni Olúwa béèrè lọ́wọ́ Káínì pé, “Níbo ni Ábélì arákùnrin rẹ wà?”Ó sì dáhùn pé, “Èmi kò mọ ibi tí ó wà, èmí ha ń ṣe olùṣọ́ arákùnrin mi bí?”

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 4