Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 4:22-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. Ṣílà náà sì bí ọmọkùnrin tí ń jẹ́ Tubali-Káínì, tí ó ń rọ oríṣìíríṣìí ohun èlò láti ara idẹ àti irin. Arábìnrin Tubali-Káínì ni Náámà.

23. Lámékì wí fún àwọn aya rẹ̀,“Ádà àti Ṣílà, ẹ tẹ́tí sí mi;ẹ̀yin aya Lámékì, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi.Mo ti pa ọkùnrin kan tí ó kọlù mí,ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó pa mí lára.

24. Bí a ó bá gbẹ̀san Káínì ní ìgbà méje,ǹjẹ́ kí a gba ti Lámékì nígbà àádọ́rin-lé-méje.”

25. Ádámù sì tún bá aya rẹ̀ lò pọ̀, ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Ṣẹ́tì, tí ó túmọ̀ sí pé, “Ọlọ́run fún mi ní ọmọkùnrin mìíràn ní ipò Ábélì tí Káínì pa.”

26. Ṣẹ́tì náà sì bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Énọ́sì.Láti àkókò náà lọ ni àwọn ènìyàn ti bẹ̀rẹ̀ sí ní ké pe orúkọ Olúwa.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 4