Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 38:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní àkókò náà, Júdà lọ kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ láti lọ dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin ará Ádúlámù kan tí ń jẹ́ Hírà.

2. Júdà sì pàdé ọmọbìnrin Kénánì kan níbẹ ẹni ti orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Súà. Ó sì fi ṣe aya, ó sì bá a lò pọ̀;

3. ó sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan, tí ó sọ orúkọ rẹ̀ ní Érì.

4. Ó sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin, ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Ónánì.

5. Ó sì tún bí ọmọkùnrin mìíràn, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Ṣélà. Ní Késíbù ni ó wà nígbà tí ó bí i.

6. Júdà sì fẹ́ aya fún Érì, àkọ́bí rẹ̀, orúkọ aya náà ni Támárì.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 38