Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 37:28-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. Nítorí náà, nigbà tí àwọn onísòwò ara Mídíánì ń kọjá, àwọn arákùnrin Jósẹ́fù fà á jáde láti inú kòtò, wọ́n sì tà á fún àwọn ará Íṣímáélì ní ogún owó wúrà, wọ́n sì mú Jósẹ́fù lọ sí ilẹ̀ Éjíbítì

29. Nígbà tí Rúbẹ́nì padà dé ibi kòtò tí ó sì ri pé Jósẹ́fù kò sí níbẹ̀ mọ́, ó fa aṣọ rẹ̀ ya pẹ̀lú ìbànújẹ́.

30. Ó padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì wí pé, “Ọmọdé-kùnrin náà kò sí níbẹ̀ mọ́! Níbo ni ẹ fẹ́ kí n wọ̀ báyìí?”

31. Nígbà náà ni wọ́n mú aṣọ Jósẹ́fù, wọ́n pa ewúrẹ́ kan, wọ́n sì tẹ aṣọ náà bọ inú ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́ náà.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 37