Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 36:24-38 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Àwọn ọmọ Ṣíbéónì:Áíyà àti Ánà. Èyí ni Ánà tí ó rí ìṣun omi gbígbóná ní inú asálẹ̀ bí ó ti ń da àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Ṣébéónì baba rẹ̀.

25. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ánà:Dísónì àti Óhólíbámà (Àwọn ọmọbìnrin ni wọn).

26. Àwọn ọmọ Dísónì ni:Hémídánì, Ésíbánì, Ítíránì àti Kéránì.

27. Àwọn ọmọ Éṣérì:Bílíhánì, Ṣááfánì, àti Ákánì.

28. Àwọn ọmọ Díṣánì ni Húsì àti Áránì.

29. Àwọn wọ̀nyí ni olórí ìdílé Hórì:Lótanì, Ṣóbálì, Ṣíbéónì, Áná,

30. Dísónì Éṣérì, àti Díṣánì. Àwọn ni olórí ìdílé àwọn ará Órì gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní ilẹ̀ Ṣéírì.

31. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọba tí ó ti jẹ ní Édómù kí ó tó di pé a ń jẹ ọba ní Ísírẹ́lì rárá:

32. Bẹ́là ọmọ Béórì jẹ ní Édómù. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Díníhábà.

33. Nígbà tí Bẹ́là kú, Jóbábù ọmọ Ṣérà ti Bósírà sì jọba ní ipò rẹ̀.

34. Nígbà tí Jóbábù kú, Úṣámù láti ilẹ̀ Témánì sì jọba ní ipò rẹ̀.

35. Nígbà tí Húṣámù kú, Hádádì ọmọ Bédádì tí ó ṣẹ́gun Mídíánì ní orílẹ̀ èdè Móábù sì jọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Áfítì.

36. Lẹ́yìn ikú Ádádì, Ṣámílà tí ó wá láti Másírékà ni ó jọba lẹ́yìn rẹ̀.

37. Sámílà sì kú, Ṣáúlì ti Réhóbótì, létí odò sì jọba lẹ́yìn rẹ̀.

38. Nígbà tí Sáúlì kú, Báálì-Hánánì ọmọ Ákíbórì jọba lẹ́yìn rẹ̀.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 36