Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 35:12-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Gbogbo ilẹ̀ tí mo fi fún Ábúráhámù àti Ísáákì ni èmi yóò fún ọ pẹ̀lú, àti fún àwọn ìran rẹ tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn.”

13. Nígbà náà ni Ọlọ́run gòkè lọ kúrò ní ibi tí ó ti ń bá a sọ̀rọ̀.

14. Jákọ́bù sì fi òkúta ṣe òpó kan sí ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀ ó sì ta ọrẹ ohun mímu (wáìnì) ní orí rẹ̀, ó sì da òróró ólífì sí orí rẹ̀ pẹ̀lú.

15. Jákọ́bù sì pe orúkọ ibi tí Ọlọ́run ti bá a sọ̀rọ̀ ní Bẹ́tẹ́lì.

16. Nígbà náà ni wọ́n ń tẹ̀ṣíwájú nínú ìrìn-àjò wọn láti Bẹ́tẹ́lì. Nígbà tí ó sì ku díẹ̀ kí wọn dé Éfúrátì, Rákélì bẹ̀rẹ̀ sí ní rọbí, ó sì ní ìdààmú púpọ̀.

17. Bí ó sì ti ń rọbí pẹ̀lú ìrora yìí, agbẹ̀bí wí fún-un pé “Má bẹ̀rù nítorí ọmọkùnrin mìíràn ni ó ń bọ̀ yìí.”

18. Bí o sì ti fẹ́ gbé ẹ̀mí mi (torí pé ó ń kú lọ), ó pe ọmọ rẹ̀ náà ní Bẹni-Ónì (ọmọ ìpọ́njú mi). Ṣùgbọ́n Jákọ́bù sọ ọmọ náà ní Bẹ́ńjámínì (ọmọ oókan àyà mi).

19. Báyìí ni Rákélì kú, a sì sin-ín sí ọ̀nà Éfúrátì (Bẹ́tílẹ́hẹ́mù).

20. Jákọ́bù sì mọ òpó (ọ̀wọ̀n) kan sí ibojì rẹ̀, òpó náà sì tọ́ka sí ojú ibojì Rákélì títí di òní.

21. Ísírẹ́lì sì ń bá ìrìn-àjò rẹ̀ lọ, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ sí Migida-Édérì (ilé-ìsọ́ Édérì).

22. Nígbà tí Ísírẹ́lì sì ń gbé ní ibẹ̀, Rúbẹ́nì wọlé tọ Bílíhà, àlè (ìyàwó tí a kò fi owó fẹ́ lọ́wọ́ àwọn òbí rẹ̀) baba rẹ̀ lọ, ó sì bá a lò pọ̀, Ísírẹ́lì sì gbọ́ ọ̀rọ̀ náà.Jákọ́bù sì bí ọmọkunrin méjìlá:

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 35