Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 34:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọjọ́ kan, Dínà ọmọbìnrin tí Líà bí fún Jákọ́bù jáde lọ bẹ àwọn ọmọbìnrin ilẹ̀ náà wò.

2. Nígbà tí Ṣékémù ọmọ ọba Hámórì ará Hífì rí i, ó mú un, ó sì fi ipá bá a lo pọ̀

3. Ọkàn rẹ sì fà sí Dínà ọmọ Jákọ́bù gan-an, ó sì fẹ́ràn rẹ̀ ó sì bá ọmọbìnrin náà sọ̀rọ̀-ìfẹ́.

4. Ṣékémù sì wí fún Hámórì bàbá rẹ̀ pé, “Fẹ́ ọmọbìnrin yìí fún mi bí aya.”

5. Nígbà tí Jákọ́bù gbọ́ ohun tí ó sẹlẹ̀ pé a fi ipá bá Dínà ọmọbìnrin òun lò pọ̀, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ rẹ̀ wà nínú pápá níbi tí wọ́n ti ń daran nítorí náà ó mú sùúrù títí tí wọ́n fi dé.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 34