Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 31:39-50 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

39. Èmi kò mú ọ̀kankan wá fún ọ rí nínú èyí tí ẹranko búburú fà ya, èmi ni ó fara mọ́ irú àdánù bẹ́ẹ̀. Ẹrankẹ́ran tí wọ́n bá sì jí lọ, lọ́sàn án tàbí lóru, ìwọ ń gba owó rẹ̀ lọ́wọ́ mi

40. Báyìí ni mo wà; oòrùn ń pa mi lọ́sàn-án, òtútù ń pa mi lóru, mo sì ń ṣe àìsùn.

41. Báyìí ni ohun gbogbo rí fún ogún ọdún tí mo fi wà nínú ilé rẹ. Ọdún mẹ́rìnlá ni mo fi sìn ọ́ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì, mo sì sìn ọ fún ọdún mẹ́fà fún àwọn ẹran ọ̀sìn, lẹ́ẹ̀mẹ́wàá ni o sì yí owó iṣẹ́ mi padà.

42. Bí ó bá ṣe pé Ọlọ́run àwọn baba mi, Ọlọ́run Ábúráhámù àti ẹ̀rù Ísáákì kò wà pẹ̀lú mi ni, ìwọ ì bá ti lé mi jáde lọ́wọ́ òfo. Ṣùgbọ́n, Ọlọ́run ti rí gbogbo ìpọ́njú mi àti iṣẹ́ àṣekára tí mo fi ọwọ mi ṣe, ó sì kìlọ̀ fún ọ lóru àná.”

43. Lábánì sì dá Jákọ́bù lóhùn, “Tèmi ni àwọn obìnrin wọ̀nyí, ọmọ mi ni àwọn ọmọ wọ̀nyí pẹ̀lú, àwọn agbo ẹran yìí, tèmi ni wọ́n pẹ̀lú. Gbogbo ohun tí o rí wọ̀nyí, tèmi ni. Kín ni mo wá le ṣe sí àwọn ọmọbìnrin wọ̀nyí àti àwọn ọmọ wọn tí wọn bí?

44. Wá, jẹ́ kí a dá májẹ̀mú pẹ̀lú ara wa, èyí yóò sì jẹ́ ẹ̀rí ní àárin wa.”

45. Jákọ́bù sì mú òkúta kan ó sì gbé e dúró bí ọ̀wọ̀n.

46. Ó sì wí fún àwọn ìbátan rẹ̀ pé, “Ẹ kó àwọn òkúta díẹ̀ jọ.” Wọ́n sì kó òkúta náà jọ bí òkítì wọ́n sì jẹun níbẹ̀.

47. Lábánì sì pe orúkọ rẹ̀ ní Akojọ òkítì ẹ̀rí, ṣùgbọ́n Jákọ́bù pè é ni Gálíídì.

48. Lábánì sì wí pé, “Òkítì yìí jẹ́ ẹ̀rí láàrin èmi àti ìwọ ní òní.” Ìdí nìyí tí a fi pe orúkọ rẹ̀ ni Gálíídì.

49. Ó tún pè é ni Mísípà nítorí, ó wí pé, “Kí Olúwa kí ó máa sọ́ èmi àti ìwọ nígbà tí a bá yà kúrò lọ́dọ̀ ara wa tán.

50. Bí o bá fìyà jẹ àwọn ọmọbìnrin mi, tàbí tí o fẹ́ aya mìíràn yàtọ̀ sí wọn, rántí pé, Ọlọ́run ń bẹ láàrin wa bí ẹlẹ́rìí bí ẹnikẹ́ni kò tilẹ̀ sí.”

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 31