Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 31:3-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Nígbà náà ni Olúwa wí fún Jákọ́bù pé, “Padà lọ sí ilẹ̀ àwọn baba à rẹ, sí ọ̀dọ̀ àwọn ará rẹ, èmi ó sì wà pẹ̀lú rẹ.”

4. Jákọ́bù sì ránṣẹ́ pe Rákélì àti Líà sí pápá níbi tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ wà.

5. Ó sì wí fún wọn pé, “Mo rí i wí pé ìwà baba yín sí mi ti yí padà sí ti tẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n Ọlọ́run baba mi wà pẹ̀lú mi.

6. Ẹ sáà mọ̀ pé, mo ti fi gbogbo agbára mi ṣiṣẹ́ fún baba yín,

7. Ṣíbẹ̀ṣíbẹ̀ baba yín ti rẹ́ mi jẹ ní ẹ̀ẹ̀mẹ́wàá ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni ó sì ti yí owó iṣẹ́ mi padà. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò jẹ́ kí ó le è pa mi lára.

8. Tí ó bá wí pé, ‘Àwọn ẹran onílà ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ’, nígbà náà ni gbogbo àwọn ẹran ń bí onílà; bí ó bá sì wí pé, ‘Àwọn ẹran oni-tótòtó ni yóò dúró fún owó iṣẹ́ rẹ’ nígbà náà ni gbogbo ẹran ń bi oní-tótòtó.

9. Bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run gba ẹran baba yín, ó sì fi fún mi”

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 31