Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 30:2-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Inú sì bí Jákọ́bù sí i, ó sì wí pé, “Èmi ha wà ní ipò Olúwa, ẹni tí ó mú ọ yàgàn bí?”

3. Nígbà náà ni Rákélì wí pé, “Bílíhà ìránṣẹ́bìnrin mi nìyìí, bá a lòpọ̀, kí ó ba à le bí ọmọ fún mi, kí èmi si le è tipaṣẹ̀ rẹ̀ ní ọmọ.”

4. Báyìí ni Rákélì fi Bílíhà fún Jákọ́bù ní aya, ó sì bá a lò pọ̀.

5. Bílíhà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan fún Jákọ́bù.

6. Rákélì sì wí pé, “Ọlọ́run ti ṣe ìdájọ́ mi; ó sì ti gbọ́ ohún ẹ̀bẹ̀ mi, ó sì fún mi ni ọmọkùnrin kan.” Nítorí ìdí èyí ni ó ṣe pe orúkọ rẹ̀ ní Dánì.

7. Bílíhà, ọmọ ọ̀dọ̀ Rákélì sì tún lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kéjì fún Jákọ́bù.

8. Nígbà náà ni Rákélì wí pé, “Mo ti bá ẹ̀gbọ́n mi ja ìjàkadì ńlá, èmi sì ti borí.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Náfítalì.

9. Nígbà tí Líà sì ri pé òun ko tún lóyún mọ́, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin, Ṣílípà fún Jákọ́bù bí aya.

10. Ṣílípà ọmọ ọ̀dọ̀ Líà sì bí ọmọkùnrin kan fún Jákọ́bù

11. Nígbà náà ni Líà wí pé, “Orí rere ni èyi!” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Gádì.

12. Ṣílípà ọmọ ọ̀dọ̀ Líà sì tún bí ọmọkùnrin kejì.

13. Nígbà náà ni Líà wí pé, “Mo ní ayọ̀ gidigidi! Àwọn ọmọbìnrin yóò sì máa pe mí ní Alábùkún fún.” Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Áṣérì.

14. Ní ọjọ́ kan, ní àkókò ìkórè ọkà jéró, Rúbẹ́nì jáde lọ sí oko, ó sì rí ọ̀gbòn mádírákì, ó sì mu un tọ Líà ìyá rẹ̀ wá. Rákélì sì wí fún Líà pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ní ara mádírákì tí ọmọ rẹ mú wá.”

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 30