Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 29:7-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Ó sì wí pé, “Kíyèsi, ilẹ̀ ò tí ì sú, kò tì í tó àkókò fún àwọn ohun ọ̀sìn láti wọ̀. Ẹ fún àwọn ẹran wọ̀nyí ní omi, kí ẹ ba à le tètè dà wọ́n padà láti jẹun.”

8. Wọ́n dá a lóhùn pé, “Àwa kì í yí òkúta kúrò ní ẹnu kànga láti pọn omi fún àwọn ẹran títí gbogbo àwọn darandaran àti àwọn ẹran yóò fi péjọ tán.”

9. Bí wọ́n sì ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́ ni Rákélì dé pẹ̀lú agbo àgùntàn baba rẹ̀, nítorí darandaran ni òun náà.

10. Nígbà tí Jákọ́bù rí Rákélì ọmọbìnrin Lábánì tí í ṣe ẹ̀gbọ́n ìyá rẹ̀, pẹ̀lú àgùntàn Lábánì, Jákọ́bù súnmọ́ kànga náà, ó sì yí òkúta kúrò lẹ́nu rẹ̀, ó sì fún àwọn ẹran arákùnrin ìyá rẹ̀ Lábánì ní omi.

11. Jákọ́bù sì fẹnu ko Rákélì ní ẹnu. Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í sọkún.

12. Jákọ́bù sì wí fún Rákélì pé ìbátan baba rẹ̀ ni òun, àti pé, òun jẹ́ ọmọ Rèbékà. Rákélì sì sáré lọ sọ fún baba rẹ̀.

13. Ní keté tí Lábánì gbúròó Jákọ́bù ọmọ arábìnrin rẹ̀, ó jáde lọ pàdé Jákọ́bù, ó dì mọ́ ọn, ó fi ẹnu kò ó ní ẹnu, ó sì mú un lọ sí ilé. Nigbà náà ni Jákọ́bù ròyìn ohun gbogbo fún un.

14. Lábánì sì wí pé, “Ẹran ara àti ẹ̀jẹ̀ ara mi ni ìwọ jẹ́.”Lẹ́yìn tí Jákọ́bù sì wà pẹ̀lú rẹ̀ fún odidi oṣù kan,

15. Lábánì wí fún Jákọ́bù pé “Bí a tilẹ̀ jẹ́ ìbátan, kò yẹ kí o máa ṣiṣẹ́ fún mi lásán láìgba ohun kankan. Sọ ohun tì ìwọ fẹ́ gbà fún iṣẹ́ tí ìwọ ń ṣe fún mi!”

16. Wàyí o, Lábánì ní ọmọbìnrin méjì, orúkọ èyí ẹgbọ́n ń jẹ́ Líà, orúkọ àbúrò sì ń jẹ́ Rákélì.

17. Líà kò ní ẹwà púpọ̀, ṣùgbọ́n Rákélì ní ẹwà gidigidi. Ojú rẹ̀ sì fanimọ́ra.

18. Jákọ́bù sì fẹ́ràn Rákélì, ó sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Èmi yóò ṣiṣẹ́ sìn ọ fún ọdún méje, bí ìwọ yóò bá fún mi ní Rákélì ọmọ rẹ ní aya.”

19. Lábánì sì dáhùn wí pé, “Ó kúkú sàn kí ń fi fún ọ, ju kí ń fi fún ẹlòmíràn lọ, nítorí wà ní ọ̀dọ̀ mi.”

20. Jákọ́bù sì ṣiṣẹ́ sin Lábánì fún ọdun méje láti fẹ́ Rákélì. Àwọn ọdún wọ̀nyí sì dà bí ọjọ́ díẹ̀ lára rẹ̀, nítorí ó fẹ́ràn rẹ̀.

21. Jákọ́bù sì wí fún Lábánì pé, “Mo ti parí àsìkò tí a jọ ṣe àdéhùn rẹ̀, nítorí náà fún mi ní aya mi, kí òun lè ṣe aya fún mi.”

22. Lábánì sì pe gbogbo ènìyàn ibẹ̀ jọ, ó sì ṣe àṣè ìyàwó fún wọ́n.

23. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di òru, Lábánì mú Líà tọ Jákọ́bù lọ. Jákọ́bù sì bá a lòpọ̀.

24. Lábánì sì fi Ṣílípà ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin fún Líà gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́.

25. Sì kíyèsi, nígbà ti ilẹ̀ mọ́, Jákọ́bù rí i pé Líà ni! Ó sì wí fún Lábánì pé, “Èwo ni iwọ́ ṣe sí mi yìí? Ṣe bí nítorí Rákélì ni mo ṣe ṣiṣẹ́ sìn ọ, èéṣe tí ìwọ́ tàn mi?”

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 29