Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 28:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nítorí náà Ísáákì pe Jákọ́bù, ó sì súre fún un, ó sì pàṣẹ fún un pé; “Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya láàrin àwọn ọmọbìnrin Kénánì.

2. Dípò bẹ́ẹ̀ lọ sí Padani-Árámù, sí ilé Bétúélì, baba ìyá rẹ, kí ìwọ kí ó sì fẹ́ aya fún ara rẹ nínú àwọn ọmọbìnrin Lábánì arákùnrin ìyá rẹ.

3. Kí Ọlọ́run Olódùmarè kí ó bùkún fún ọ, kí ó sì mú ọ bí sí i, kí ó sì mú ọ pọ̀ sí i ní iye títí tí ìwọ yóò di àgbájọ àwọn ènìyàn.

4. Kí Ọlọ́run kí ó fún ìwọ àti irú ọmọ rẹ ní ìre tí ó sú fún Ábúráhámù, kí ìwọ kí ó le gba ilẹ̀ níbi tí a ti ń ṣe àtìpó yìí, ilẹ̀ tí Ọlọ́run ti fi fún Ábúráhámù.”

5. Bẹ́ẹ̀ ni Ísáákì sì rán Jákọ́bù lọ. Ó sì lọ sí Padani-Árámù, lọ́dọ̀ Lábánì ọmọ Bétúélì, ará Árámíà, tí í ṣe arákùnrin Rèbékà ìyá Jákọ́bù àti Ísọ̀.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 28