Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 25:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ábúráhámù sì tún fẹ́ aya mìíràn, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Kétúrà.

2. Ó sì bí Ṣímúránì, Jókíṣánì, Médánì, Mídíánì, Ísíbákù, àti Ṣúà

3. Jókíṣánì ni baba Ṣébà àti Dédánì, àwọn ìran Dédánì ni àwọn ara Áṣúrímù, Létúsì àti Léúmínù.

4. Àwọn ọmọ Mídíánì ni Éfánì, Éférì, Ánókù, Ábídà àti Élídà. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ìran Kétúrà.

5. Ábúráhámù sì fi ohun gbogbo tí ó ní fún Ísáákì.

6. Ṣùgbọ́n kí o tó kú, ó fún àwọn ọmọ tí àwọn àlè rẹ̀ bí fún un ní ẹ̀bùn, ó sì lé wọn jáde lọ fún Ísáákì ọmọ rẹ sí ilẹ̀ ìlà oòrùn.

7. Gbogbo àpapọ̀ ọdún tí Ábúráhámù lò láyé jẹ́ igba ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n (175).

8. Ábúráhámù sì kú ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ó dàgbà, ó darúgbó kí ó tó kú. A sì sin in sí ibojì àwọn ènìyàn rẹ̀.

9. Àwọn ọmọ rẹ̀, Ísáákì àti Ísímáélì sì sin-in sínú ihò àpáta ni Mákípélà ní ẹ̀gbẹ́ Mámúrè, ní oko Éfúrónì ọmọ Ṣóhárì ara Hítì

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 25