Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 24:10-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Ìránṣẹ́ náà sì mú ràkunmí mẹ́wàá, pẹ̀lú onírúurú ohun dáradára láti ọ̀dọ̀ olúwa rẹ̀, ó sì dìde ó sì lọ sí Aramu-Náháráímù, sí ìlú Náhórì,

11. Ó sì mú àwọn ràkunmí náà kúnlẹ̀ nítòòsí kànga lẹ́yìn ìlú, ó ti ń di ọwọ́ ìrọ̀lẹ̀ ní àkókò tí àwọn obìnrin máa ń lọ pọn omi.

12. Ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Ábúráhámù olúwa à mi; jẹ́ kí n ṣe àṣeyọrí lónìí, sì fi àánú hàn fún Ábúráhámù olúwa mi.

13. Kíyèsí i, mo dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ yìí, àwọn ọmọbìnrin ìlú yìí sì ń jáde wá pọn omi.

14. Jẹ́ kí ó ṣe pé nígbà tí mo bá wí fún ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin pe, ‘Jọ̀wọ́ sọ ládugbó rẹ kalẹ̀, kí n le mu omi,’ tí ó bá sì wí pé, ‘mu un, èmi ó sì fún àwọn ràkunmí rẹ náà mu pẹ̀lú,’ jẹ́ kí ó ṣe èyí tí o yàn fún ìránṣẹ́ rẹ Ísáákì. Nípa èyí ni n ó fi mọ̀ pé o ti fi àánú hàn fún olúwa mi.”

15. Kí o tó di pé, ó parí àdúrà, Rèbékà dé pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀. Ọmọ Bétúélì ni. Bétúélì yìí ni Mílíkà bí fún Náhórì arákùnrin Ábúráhámù.

16. Ọmọbìnrin náà rẹwà, wúndíá ni, kò sì tíì mọ ọkùnrin, ó lọ sí ibi ìsun omi náà, ó sì pọn omi sínú ìkòkò omi, ó sì gbé e, ó ń gòkè bọ̀ kúrò níbi omi.

17. Ìránṣẹ́ náà súré lọ pàdé e rẹ̀ ó sì wí fun un pé, “Jọ̀wọ́ fún mi ni omi díẹ̀ nínú ìkòkò omi rẹ.”

18. Òun náà dáhùn pé, “Mu, olúwa mi,” ó sì yára sọ ìkòkò omi náà ka ọwọ́ rẹ̀, ó sì fún-un mu.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 24