Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 18:15-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ẹ̀rù sì ba Ṣárà, ó sì sẹ́ pé òun kò rẹ́rìn-ín.Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún-un pé, “Dájúdájú ìwọ rẹ́rín-ín.”

16. Nígbà tí àwọn ọkùnrin náà dìde láti máa lọ, wọn kọjú sí ọ̀nà Ṣódómù, Ábúráhámù sì sìn wọ́n dé ọ̀nà.

17. Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Ǹjẹ́ èmi yóò ha pa ohun tí mo fẹ́ ṣe mọ́ fún Ábúráhámù bí?

18. Dájúdájú Ábúráhámù yóò sá à di orilẹ̀ èdè ńlá àti alágbára, a ó sì tipaṣẹ̀ rẹ̀ bùkún gbogbo orílẹ̀ èdè ayé.

19. Nítorí tí èmi ti yàn án láti kọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ará ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, láti máa pa ọ̀nà Olúwa mọ nípa ṣíṣe olóòtọ́ àti olódodo: kí Olúwa le è mú ìlérí rẹ̀ fún Ábúráhámù ṣẹ.”

20. Olúwa sì wí pé, igbe Ṣódómù àti Gòmórà pọ̀ púpọ̀ àti pé ẹ̀ṣẹ̀ wọn burú jọjọ.

21. “Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ síbẹ̀ láti ṣe ìwádìí igbe tí ó dé sí etí ìgbọ́ mi nípa wọn, kí èmi sì mọ òtítọ́ tí ó wà níbẹ̀.”

22. Àwọn ọkùnrin náà yí padà, wọ́n sì ń lọ sí ìhà Ṣódómù. Ṣùgbọ́n Ábúráhámù dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa.

23. Nígbà náà ni Ábúráhámù súnmọ́ ọ̀dọ̀ Olúwa, ó sì wí pé, “Ìwọ yóò ha pa ènìyàn rere àti ènìyàn búrurú run papọ̀ bí?”

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 18