Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 12:15-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Nígbà tí àwọn ìjòyè Fáráò sì rí i, wọ́n ròyìn rẹ̀ níwájú u Fáráò, Wọ́n sì mú un lọ sí ààfin,

16. Ó sì kẹ́ Ábúrámù dáradára nítorí Ṣáráì, Ábúrámù sì ní àgùntàn àti màlúù, akọ àti abo, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin, pẹ̀lú u ràkunmí.

17. Olúwa sì rán àjàkálẹ̀-àrùn búburú sí Fáráò àti ilé rẹ̀, nítorí Sáráì aya Ábúrámù.

18. Nítorí náà Fáráò ránṣẹ́ pe Ábúrámù, ó sì wí fun pé, “Èwo ni ìwọ ṣe sí mi yìí? Kí n ló dé tí ìwọ kò sọ fún mi pé aya rẹ ní í ṣe?

19. Èéṣe tí o fi wí pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ tí èmi sì fi fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí aya? Nítorí náà nísinsin yìí, aya rẹ náà nìyí, mú un kí sì o máa lọ.”

20. Nígbà náà ni Fáráò pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ nípa Ábúrámù, wọ́n sì lé e jáde ti òun ti aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 12