Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 11:8-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Ọlọ́run sì tú wọn ká sórí ilẹ̀ gbogbo, wọ́n sì ṣíwọ́ ìlú náà tí wọn ń tẹ̀dó.

9. Ìdí èyí ni a fi pè é ní Bábílónì nítorí ní ibẹ̀ ni Ọlọ́run ti da èdè gbogbo ayé rú, tí ó sì tú àwọn ènìyàn ká sí gbogbo orí ilẹ̀ ayé.

10. Wọ̀nyí ni ìran ṢémùỌdún méjì lẹ́yìn ìkún omi, tí Ṣémù pé ọgọ́rùn-ún ọdún (100) ni ó bí Áfákísádì.

11. Lẹ́yìn tí ó bí Áfákísádì, ó tún wà láàyè fún ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọdún (500), ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.

12. Nígbà tí Áfákísádì pé ọdún marùndínlógójì (35) ni ó bí Ṣélà.

13. Ó sì wà láàyè fún ọdún mẹ́talénírínwó (403) lẹ́yìn tí ó bí Ṣélà, ó sì bí àwọn ọmọbìnrin àti àwọn ọmọkùnrin mìíràn.

14. Nígbà tí Ṣélà pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún (30) ni ó bí Ébérì.

15. Ó sì wà láàyè fún ọdún mẹ́talénírinwó (403) lẹ́yìn tí ó bí Ébérì, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.

16. Ébérì sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n (34), ó sì bí Pélégì.

17. Ébérì sì wà láàyè fún irínwó-ó-lé-ọgbọ̀n ọdún (430) lẹ́yìn tí ó bí Pélégì, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.

18. Nígbà tí Pélégì pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún (30) ni ó bí Réù.

19. Ó sì tún wà láàyè fún igba-ó-lé-mẹ́sàn án ọdún (209) lẹ́yìn tí ó bí Réù, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.

20. Nígbà tí Réù pé ọdún méjìlélọ́gbọ̀n (32) ni ó bí Ṣérúgì.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 11