Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 10:6-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Àwọn ọmọ Ámù ni:Kúsì, Mísíráímù, Fútì àti Kénánì.

7. Àwọn ọmọ Kúsì ni:Ṣébà, Háfílà, Ṣábátà, Rámà, àti Ṣábítékà.Àwọn ọmọ Rámà ni:Ṣébà àti Dédánì.

8. Kúsì sì bí Nímúrọ́dù, èyí tí ó di alágbára àti jagunjagun ní ayé.

9. Ó sì jẹ́ ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa; nítorí náà ni a ṣe ń wí pé, “Bí Nímúrọ́dù-ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa.”

10. Ìjọba rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni Bábílónì, Érékì, Ákádì, Kálínéhì, gbogbo wọn wà ní ilẹ̀ Ṣínárì.

11. Láti ilẹ̀ náà ni ó ti lọ sí dé Áṣíríà, níbi tí ó ti tẹ ìlú Nínéfè, Réhóbótì àti Kálà,

12. àti Résínì, tí ó wà ní àárin Nínéfè àti Kálà, tí ó jẹ́ ìlú olókìkí.

13. Mísíráímù ni baba ńlá àwọn aráLúdì, Ánámì, Léhábì, Náfítúhímù.

14. Pátírúsímù, Kásílúhímù (èyí tí í ṣe baba ńlá àwọn Fílístínì) àti Káfítórímù.

15. Kénánì ni baba àwọn aráSídónì (èyi ni àkọ́bí rẹ̀), àti àwọn ara Hítì.

16. Àwọn ará Jébúsì, Ámórì, Gágásì.

17. Hífì, Áríkì, Sínì,

18. Áfádì, Ṣémárì àti Hámátì.Nígbà tí ó ṣe, àwọn ẹ̀yà Kénánì tàn kálẹ̀.

19. Ààlà ilẹ̀ àwọn ará Kénánì sì dé Ṣídónì, lọ sí Gérárì títí dé Gásà, lọ sí Sódómù, Gòmórà, Ádímà àti Ṣébóìmù, títí dé Láṣà.

20. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ámù, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, àti èdè wọn, ní ìpínlẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.

21. A bí àwọn ọmọ fún Ṣémù tí Jáfétì jẹ́ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin: Ṣémù sì ni baba gbogbo àwọn ọmọ Ébérì.

22. Àwọn ọmọ Ṣémù ni:Élámù, Ásọ̀, Áfákísádì, Lúdì àti Árámù.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 10