Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 16:14-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Òkìkí rẹ sì kàn káàkiri orílẹ̀ èdè nítorí ẹwà rẹ, nítorí dídán tí mo fi ṣe ẹwà rẹ láṣe pé, ni Olúwa Ọlọ́run wí.

15. “ ‘Ṣùgbọ́n, o gbẹ́kẹ̀lé ẹwà rẹ, o sì di alágbérè nítorí òkìkí rẹ. O sì fọ́n oju rere rẹ káàkiri sórí ẹni yòówù tó ń kọjá lọ, ẹwà rẹ sì di tìrẹ.

16. O mú lára àwọn aṣọ rẹ, láti rán aṣọ aláràbarà fún ibi giga òrìṣà tí o ti ń ṣàgbèrè. Èyí kò yẹ kó rí bẹ́ẹ̀, tàbí kó tilẹ̀ ṣẹlẹ̀ rárá.

17. O tún mú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ dáradára tí mo fi wúrà àti fàdákà ṣe fún ọ láti fi yá ère ọkùnrin tí ó ń bá ọ ṣe àgbèrè papọ̀.

18. O sì wọ ẹ̀wù oníṣẹ́ ọnà rẹ fún wọn, o sì tún gbé òróró àti tùràrí mi sílẹ̀ níwájú wọn.

19. O tún gbé oúnjẹ tí mo fún ọ-ìyẹ̀fún dáradára, òróró àti oyin-fún wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun olóòórùn dídùn; ohun tó ṣẹlẹ̀ nìyìí, ni Olúwa Ọlọ́run wí.

20. “ ‘Àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin tí o bí fún mi lo ti fi rúbọ bí oúnjẹ fún àwọn òrìṣà. Ṣé ìwà àgbèrè rẹ kò ha tó bí?

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 16