Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ísíkẹ́lì 11:20-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.

21. Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sórí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”

22. Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn ògo Ọlọ́run Ísírẹ́lì sì wà lókè orí wọn.

23. Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrin ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà oòrùn ìlú náà.

24. Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi lójú ìran lọ bá àwọn ìgbèkùn Bábílónì. Ìran tí mo rí sì parí,

25. Mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní Ìgbèkùn.

Ka pipe ipin Ísíkẹ́lì 11