Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hósíà 4:13-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Wọ́n ń rúbọ lórí àwọn òkè ńlá,Wọ́n sì ń sun ọrẹ tùràrí lórí àwọn òkè kékeréLábẹ́ igi óákù, àti igi pópúlárìàti igi ẹlimuati onírúurú igi tí ìbòjú rẹ̀ dáraNítorí náà àwọn ọmọbìnrin yín yóò ṣe àgbèrèàti àwọn àfẹ́sọ́nà yín yóò ṣe àgbèrè.

14. “Èmi kò ní jẹ àwọn ọmọbìnrin yínníyà nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrètàbí àwọn àfẹ́sọ́nà ọmọ yín,nígbà tí wọ́n bá ṣe àgbèrènítorí pé àwọn ọkùnrin pàápàá ń bá alágbèrè kẹ́gbẹ́.Wọ́n sì ń rúbọ pẹ̀lú àwọn alágbèrè ilé òrìṣà.Nítorí náà, ènìyàn tí kò bá ní òye yóò parun!

15. “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o ṣe àgbèrè ìwọ Ísírẹ́lìÌdájọ́ yìí wà fún un yín Ẹ má ṣe jẹ́ kí Júdà di ẹlẹ́bi.“Ẹ má ṣe lọ sí Gílígálì.Ẹ má sì ṣe gòkè lọ sí Bẹti-ÁfénìẸ má sì búra pé, ‘Bí Olúwa ti wà láàyè nítòótọ́!’

16. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ṣe agídíbí alágídí ọmọ màlúùBáwo wá ni Olúwa ṣe fẹ́ bọ́ wọnbí àgùntàn ní pápá oko tútù?

17. Éfúráímù ti darapọ̀ mọ́òrìṣà Ẹ fi sílẹ̀!

Ka pipe ipin Hósíà 4