Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Hósíà 13:5-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Mo ṣe ìtọ́jú rẹ ní ihàní ilẹ̀ tí ó gbẹ tí kò ní omi

6. Wọn ni ìtẹ́lọ́rùn nígbà tí mo fún wọn ní oúnjẹNígbà tí wọ́n ní ìtẹ́lọ́rùn tan wọ́n di agbéragaNígbà náà ni wọ́n sì gbàgbé mi.

7. Nítorí náà, Èmi yóò dìde sí wọn bí i kìnnìúnÈmi yóò farapamọ́ dè wọ́n lọ́nà bí i ẹkùn.

8. Béárì igbó tí a já ọmọ rẹ̀ gbàÈmi yóò bá wọn jà bí?Èmi yóò sì fà wọ́n yabí ìgbà tí ẹkùn bá fa ara wọn ya.

9. “A ti pa ọ́ run, ìwọ Ísírẹ́lìnítorí pé ìwọ lòdì sí mi ìwọ lòdì sí olùrànlọ́wọ́ rẹ.

10. Níbo ni ọba rẹ gbé wà nìsisin yìí kí ó bá à le gbà ọ là?Níbo ni àwọn olórí ìlú yín wà,àwọn tí ẹ sọ pé,‘Fún wa ní ọba àti ọmọ aládé’?

11. Nítorí èyí nínú ìbínú mi ni mo fún un yín lọ́baNinú ìbínú gbígbóná mi, Mo sì mú un kúrò

12. Ẹ̀bi Éfúráímù ni a tí ko jọgbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ wà nínú àkọsílẹ̀

13. Ìrora bí obìnrin tó fẹ́ bímọ ti dé bá aṢùgbọ́n ó jẹ́ ọmọ tí kò lọ́gbọ́nNígbà tí àsìkò tó,ó kọ̀ láti jáde síta láti inú.

14. “Èmi yóò rà wọ́n padà kúrò lọ́wọ́ agbára isà òkú.Èmi yóò rà wọ́n padà lọ́wọ́ ikúIkú, àjàkálẹ̀-àrùn rẹ dà?Isà okú, ìparun rẹ dà?“Èmi kò ní ṣàánú mọ́.

15. Bí ó tilẹ̀ gbilẹ̀ láàrin àwọn arákùnrin rẹ̀afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn láti ọ̀dọ̀ Olúwa yóò wá,Yóò fẹ́ wá láti inú asálẹ̀orísun omi rẹ̀ yóò gbẹkànga rẹ̀ yóò gbẹpẹ̀lú olè yóò fọ́ ilé ẹrùàti gbogbo ilé ìṣúra rẹ̀

16. Ará Sámáríà gbọdọ̀ ru ẹ̀bi wọn,nítorí pé wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí Ọlọ́run wọn.Wọn ó ti ipa idà ṣubú;a ó fọ́ àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀,A ó sì la àwọn aboyún wọn nínú.”

Ka pipe ipin Hósíà 13