Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹ́sírà 8:1-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Wọ̀nyí ni àwọ̀n olórí ìdílé àti àwọn tí ó fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn tì wọn gòkè pẹ̀lú mi làti Bábílónì ní àkókò ìjọba Aritaṣéṣéṣì ọba:

2. Nínú àwọn ọmọ Fínéhásì, Gásómù;nínú àwọn ọmọ Ítamárì, Dáníẹ́lì;nínú àwọn ọmọ Dáfídì, Hátúsì,

3. nínú àwọn ọmọ Ṣekaníáyà;nínú àwọn ọmọ Párósì, Ṣekaríáyà, àti pé àádọ́jọ (150) ọkùnrin fi orùkọ sílẹ̀ pẹ̀lú rẹ;

4. nínú àwọn ọmọ Pahati-Móábù, Elehóénáyì ọmọ Seraíyà àti àwọn igba (200) ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

5. nínú àwọn ọmọ Ṣátù, Ṣekaníáyà ọmọ Jahasíélì àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún (300) ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

6. nínú àwọn ọmọ Ádínì, Ébédì ọmọ Jónátanì, àti àádọ́ta (50) ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

7. nínú àwọn ọmọ Élámù, Jésáíyà ọmọ Ataláyà àwọn àádọ́rin (70) ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

8. nínú àwọn ọmọ Ṣéfátayà, Ṣébádáyà ọmọ Míkẹ́lì, àti ọgọ́rin (80) ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

9. nínú àwọn ọmọ Jóábù, Ọbádáyà ọmọ Jéhíélì àti ogun-ó-lugba-ó-din méjì (218) ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

10. nínú àwọn ọmọ Bánì, Ṣélómútì ọmọ Jósífáyà àti ọgọ́jọ 160 ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

11. nínú àwọn ọmọ Bébáì, Sakaráyà ọmọ Bébáì àti ọkúnrin 45 méjìdínlọ́gbọ̀n pẹ̀lú rẹ̀;

12. nínú àwọn ọmọ Ásígádì, Johánánì ọmọ Hákátanì, àti àádọ́fà (110) ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;

13. nínú àwọn ọmọ Ádóníkámù, àwọn ti ó gbẹ̀yìn, tì orùkọ wọn ń jẹ̀ Élífélétì, Jéúélì àti Ṣémáyà, àti ọgọ́ta (60) ọkúnrin pẹ̀lú wọn;

14. Nínú àwọn ọmọ Bígífáyì, Hútayì àti Ṣákúrì, àti àádọ́rin 70 ọkúnrin pẹ̀lú wọn.

15. Èmi kó wọn jọ pọ̀ si etí odò ti ń ṣàn lọ sí Áháfà, a pàgọ́ síbẹ̀ fùn odidi ọjọ́ mẹ́ta, nígbà ti mo wo àárin àwọn ènìyàn àti àárin àwọn àlùfáà, ń kò ri ọmọ Léfì kankan níbẹ̀.

16. Nígbà náà ni mo pe Élíásérì, Áríélì, Ṣemanáyà, Elinátanì, Járíbù, Elinátánì, Nátanì, Ṣakaráyà, àti Mésúlámù, ti wọ̀n jẹ̀ olórí, àti Jóíáríbù àti Elinátanì ti wọ̀n jẹ́ onímọ̀ ìjìnlẹ̀,

Ka pipe ipin Ẹ́sírà 8