Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹ́sírà 3:10-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Nígbà tí àwọn ọ̀mọ̀lé gbé ìpìlẹ̀ ilé Olúwa kalẹ̀, àwọn àlùfáà nínú aṣọ iṣẹ́ àlùfáà wọn pẹ̀lú fèrè, àti àwọn ará Léfì (Àwọn ọmọ Ásáfù) pẹ̀lú Kíńbálì, dúró ní ipò wọn láti yin Olúwa, bí Dáfídì ọba Ísírẹ́lì ti fi lélẹ̀.

11. Pẹ̀lú ìyìn àti ọpẹ́ ni wọ́n kọrin sí Olúwa:“Ó dára;ìfẹ́ rẹ̀ sí Ísírẹ́lì dúró títí láé.”Gbogbo àwọn ènìyàn sì fi ohùn ariwo ńlá yin Olúwa, nítorí tí a ti fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lélẹ̀.

12. Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ lára àwọn àgbà àlùfáà àti àwọn ará Léfì àti àwọn olórí ìdílé, tí ó ti rí tẹ́ḿpìlì Olúwa ti tẹ́lẹ̀, wọ́n sunkún kíkorò nígbà tí wọ́n rí ìpìlẹ̀ tẹ́ḿpìlì Olúwa yìí tí wọ́n fi lélẹ̀, nígbà tí ọ̀pọ̀ kígbe fún ayọ̀.

13. Kò sí ẹni tí ó le mọ́ ìyàtọ̀ láàárin igbe ayọ̀ àti ẹkún, nítorí tí ariwo àwọn ènìyàn náà pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́. Wọ́n sì gbọ́ igbe náà ní ọ̀nà jínjìn réré.

Ka pipe ipin Ẹ́sírà 3