Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ẹkún Jeremáyà 5:16-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Adé ti sí kúrò ní orí waÈgbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.

17. Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa,nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.

18. Fún òkè Síónì tí ó ti di ahorolórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.

19. Ìwọ, Olúwa, jọba títí láé;ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.

20. Kí ló dé tí o n gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà?Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?

21. Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà;mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbà a nì

22. Àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátátí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.

Ka pipe ipin Ẹkún Jeremáyà 5