Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 9:21-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Ṣùgbọ́n àwọn ti kò kà ọ̀rọ̀ Olúwa sí fi àwọn ẹrú wọn àti àwọn ẹran-ọ̀sìn wọn sílẹ̀ ni pápá.

22. Olúwa sọ fún Mósè pé, “Gbé ọwọ́ rẹ sókè sí ọ̀run kí yìnyín bá à lè rọ̀ sí orí gbogbo ilẹ̀ Éjíbítì, sí orí ènìyàn àti ẹranko, àti sí orí gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ó wà ni inú oko.”

23. Nígbà tí Mósè gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè sí ojú ọ̀run, Olúwa rán àrá àti yìnyín, mọ̀nàmọ́ná sì bù sí orí ilẹ̀. Olúwa rọ òjò yìnyín sí orí ilẹ̀ Éjíbítì;

24. Yìnyín rọ̀, mọ̀nàmọ́ná sì bẹ̀rẹ̀ sí bù sí orí ilẹ̀ èyí ni ó tí ì buru jù ti ó ṣẹlẹ̀ láti ìgbà ti Éjíbítì ti di orílẹ̀ èdè.

Ka pipe ipin Ékísódù 9