Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 7:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mósè pé, “Wò ó, èmi ti ṣe ọ bí Ọlọ́run fún Fáráò, Árónì arákùnrin rẹ ni yóò jẹ́ wòlíì (agbẹnusọ) rẹ.

2. Ìwọ yóò sì sọ ohun gbogbo tí èmi ti pàṣẹ fún ọ, Árónì arákùnrin rẹ yóò sí sọ fún Fáráò kí ó jẹ́ kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jáde kúrò ni ilẹ̀ rẹ̀.

3. Ṣùgbọ́n èmi yóò ṣé Fáráò lọ́kàn le. Bí mo tilẹ̀ ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ àmì àti ìyanu ni Éjíbítì,

4. ṣíbẹ̀ òun kì yóò fi etí sí ọ. Nígbà náà ni èmi yóò gbé ọwọ́ mi lé Éjíbítì, pẹ̀lú agbára ìdájọ́ ńlá mi ni èmi yóò mú àwọn ènìyàn mi Ísírẹ́lì jáde ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́.

Ka pipe ipin Ékísódù 7