Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 6:25-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Élíásárì ọmọ Árónì fẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọbìnrin Pútíẹ́lì ní ìyàwó, ó sì bí Fínéhásì fún un.Ìwọ̀nyí ni olórí àwọn Léfì ni ìdílé ìdílé.

26. Árónì àti Mósè yìí kan náà ni Olúwa sọ fún pé, “Ẹ kó àwọn ará Ísírẹ́lì jáde kúrò ni ilẹ̀ Éjíbítì ní ìsọ̀rí ìsọ̀rí.”

27. Àwọn ni ó bá Fáráò ọba Éjíbítì sọ̀rọ̀ nípa kíkó àwọn ará Ísírẹ́lì jáde kúrò ni Éjíbítì, àní Mósè àti Árónì yìí kan náà ni.

28. Nígbà tí Olúwa bá Mósè sọ̀rọ̀ ni Éjíbítì,

29. Ó ni “Èmi ni Olúwa. Sọ ohun gbogbo ti mo ti sọ fún ọ fún Fáráò ọba Éjíbítì.”

30. Ṣùgbọ́n Mósè sì wí ní iwájú Olúwa pé, “Níwọ̀n ìgbà ti mo jẹ́ akólòlò, ọ̀nà dà ti Fáráò yóò ṣe fi etí sí mi?”

Ka pipe ipin Ékísódù 6