Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 35:3-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ẹ má se dáná kankan ní ibùgbé yín ní ọjọ́ ìsinmi.”

4. Mósè sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pa láṣẹ:

5. Láti inú ohun tí ẹ ni ni kí ẹ ti mú ọrẹ fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ọ́ bá fẹ́ ni kí ó mú ọrẹ fún Olúwa ní ti wúrà, fàdákà àti idẹ;

6. aṣọ aláró, elésèé àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára; àti irun ewúrẹ́;

7. awọ àgbò tí a kùn ní pupa àti awọ màlúù; odò igi kaṣíá;

8. òróró ólífì fún títan iná; olóòórùn fún òróró ìtasórí, àti fún tùràrí dídùn;

9. Òkúta óníkìsì àti òkúta tí a tò sí ẹ̀wù èfòdì àti igbáàyà.

10. “Gbogbo ẹni tí ó ní ọgbọ́n láàrin yín, kí ó wa, kí ó sì wá se gbogbo ohun tí Olúwa ti pa láṣẹ:

11. Àgọ́ náà pẹ̀lú àgọ́ rẹ àti ìbòrí rẹ̀, kọ́kọ́rọ́ rẹ̀, pákó rẹ̀, ọ̀pá rẹ̀, ọ̀wọ́n rẹ̀ àti ihò ìtẹ̀bọ̀ rẹ̀;

Ka pipe ipin Ékísódù 35