Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 3:18-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. “Àwọn àgbààgbà Ísírẹ́lì yóò fetí sílẹ̀ sí ohùn rẹ. Nígbà náà ni ìwọ, àti àwọn àgbààgbà yóò jọ tọ ọba Éjíbítì lọ, ẹ ó sì wí fún un pé, ‘Olúwa, Ọlọ́run àwọn ará Hébérù ti pàdé wa. Jẹ́ kí a lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú ihà láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run.’

19. Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ọba Éjíbítì kò ní jẹ́ kí ẹ lọ bí kò ṣe pé ọwọ́ ńlá Ọlọ́run wà ni ara rẹ̀.

20. Nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mí láti lu àwọn ará Éjíbítì pẹ̀lú gbogbo ohun ìyanu tí èmi yóò ṣe ni àárin wọn. Lẹ́yìn náà, òun yóò jẹ́ kí ẹ máa lọ.

Ka pipe ipin Ékísódù 3