Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 3:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mósè ń sọ́ agbo ẹran Jẹ́tírò baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Mídíánì. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jínjìn nínú ihà. Ó dé Hórébù, òkè Ọlọ́run.

2. Níbẹ̀ ni ańgẹ́lì Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́ iná ti ń jó láàrin igbó. Mósè rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run

3. Nígbà náà ni Mósè sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”

4. Nígbà tí Olúwa rí i pe Mósè ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárin igbó náà, “Mósè! Mósè!!”Mósè sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nì yìí.”

Ka pipe ipin Ékísódù 3