Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 25:34-40 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

34. Ní ara ọ̀pá fìtílà ni kọ́ọ̀bù mẹ́rin ti a se gẹ́gẹ́ bí òdòdó alímọńdì ti ó ni ìṣọ àti ìtànná yóò wà.

35. Ìṣọ kan yóò wà lábẹ́ méjì àkọ́kọ́ tí ó yọ lára ọ̀pá fìtílà, ìṣọ kejì lábẹ́ ẹ̀ka méjì kejì, ìṣọ kẹta ní abẹ́ ẹ̀ka mẹ́ta kẹta: ẹ̀ka mẹ́fà ní àpapọ̀.

36. Ìṣọ àti ẹ̀ka yóò di ara kan náà pẹ̀lú òpó fìtílà ti a fi ojúlówó wúrà ti a lù ṣe.

37. “Nígbà náà ni ìwọ yóò se fítílà méje. Ìwọ yóò sì gbe ka orí rẹ̀, kí wọn bá a lè tan iná sí iwájú rẹ̀.

38. Ike ọ̀pá àbẹ́là àti ọpọ́n agogo gbọdọ̀ jẹ́ èyí tí a fi ojúlówó wúrà ṣe.

39. Ìwọ̀n ojúlówó wúrà ti ó tó talẹ́ǹtì kan ni a gbọdọ̀ fi se ọ̀pá fìtílà àti àwọn ti ó so mọ́ ọn.

40. Rí i pé ó ṣe gẹ́gẹ́ bí bátànì ti mo fihàn ọ́ ni orí òkè.

Ka pipe ipin Ékísódù 25