Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 23:3-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúṣáájú sí talákà nínú ẹjọ́ rẹ̀.

4. “Bí ìwọ bá se alábàápàdé akọ màlúù tàbí akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ọ̀ta rẹ tí ó sinà lọ, rí i dájú pé o mú un padà wá fún un.

5. Bí ìwọ bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹnìkan tí ó koríra rẹ tí ẹrù subú lé lórí, má ṣe fi í sílẹ̀ bẹ́ẹ̀; rí i dájú pé o ran án lọ́wọ́ nípa rẹ.

6. “Ìwọ kò gbọdọ̀ du aláìní ní ìdájọ́ òdodo.

7. Má ṣe lọ́wọ́ nínú ẹ̀sùn èké, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ pa aláìṣẹ̀ tàbi olódodo ènìyàn, nítorí èmi kò ní dá ẹlẹ́bí láre.

8. “Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, nítorí àbẹ̀tẹ́lẹ̀ máa ń fọ àwọn tó ríran lójú, a sì yí ọ̀rọ̀ olódodo po.

9. “Ìwọ kò gbọdọ pọ́n àlejò kan lójú sa ti mọ inú àlejò, nítorí ẹ̀yin náà ti jẹ́ àlejò ní ilẹ̀ Éjíbítì.

Ka pipe ipin Ékísódù 23