Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 19:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní oṣù kẹ́ta tí àwọn Ísírẹ́lì jáde kúrò ni ilẹ̀ Éjíbítì, ni ọjọ́ náà gan an ni wọ́n dé ihà Ṣínáì.

2. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n gbéra kúrò ní Réfídímù, wọ́n wọ ijù Ṣínáì, wọ́n sì tẹ̀dó ṣíbẹ̀ ní iwájú òkè Ṣínáì.

3. Mósè sì gòkè tọ Ọlọ́run lọ. Olúwa sì ké pè é láti orí òkè náà wá pé, “Èyí ni ìwọ yóò sọ fún ilé Jákọ́bù àti ohun tí ìwọ yóò sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì:

4. ‘Ẹ̀yin ti rí ohun tí mo ti ṣe sí àwọn ará Éjíbítì, àti bí mo ti gbé e yín ní apá ìyẹ́ idì.

5. Nísinsìn yìí, bí ẹ̀yin bá ṣe ìgbọ́rán sí mi dé ojú àmì, tí ẹ sì pa májẹ̀mu mi mọ́, nígbà náà ni ẹ̀yin ó jẹ́ ìṣúra fún mi ju gbogbo orílẹ̀ èdè yóòkù lọ. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gbogbo ayé ni tèmi.

Ka pipe ipin Ékísódù 19