Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 17:9-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Mósè sì sọ fún Jọ́súà pé, “Yàn lára àwọn ọkùnrin fún wa, kí wọn ó sì jáde lọ bá àwọn ará Ámélékì jà. Ní ọ̀la, èmi yóò dúró ni orí òkè pẹ̀lú ọ̀pá Ọlọ́run ní ọwọ́ mi.”

10. Jósúà se bí Mósè ti wí fún un, ó sì bá àwọn ará Ámélékì jagun; nígbà tí Mósè, Árónì àti Húrì lọ sí orí òkè náà.

11. Níwọ̀n ìgbà tí Mósè bá gbé apá rẹ̀ sókè, Ísírẹ́lì n borí ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá sì rẹ apá rẹ̀ sílẹ̀, Ámélékì a sì borí.

12. Ṣùgbọ́n apá ń ro Mósè; Wọ́n mú òkúta, wọ́n sì fi sí abẹ́ rẹ̀, ó sì jókòó lé òkúta náà: Árónì àti Húrì sì mu ní apá rẹ̀, ọ̀kan ní apá ọ̀tún àti èkejì ni apá òsì; apá rẹ̀ méjèèjì sì dúró gangan títí di ìgbà ti òòrùn wọ.

13. Jósúà sì fi ojú idà sẹ́gun àwọn ará Ámélékì.

Ka pipe ipin Ékísódù 17