Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 17:14-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Olúwa sì sọ fun Mósè pé. “Kọ èyí sì inú ìwé fún ìrántí, kí o sì sọ fún Jóṣúà pẹ̀lú; nítorí èmi yóò pa ìràntí Ámélékì run pátapáta kúrò lábẹ́ ọ̀run.”

15. Mósè sì tẹ́ pẹpẹ kan, ó sì sọ orúkọ pẹpẹ náà ní Olúwa ni àṣíá mi (Jóhéfà-Nisì).

16. Ó wí pé, “A gbé ọwọ́ sókè sí ìtẹ́ Olúwa. Olúwa yóò bá Ámélékì jagun láti ìran dé ìran.”

Ka pipe ipin Ékísódù 17