Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Ékísódù 13:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Olúwa sọ fún Mósè pé,

2. “Ẹ ya àwọn àkọ́bí yín ọkùnrin ṣọ́tọ̀ fún mi. Èyí ti ó bá jẹ́ àkọ́bí láàrin àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jẹ́ tèmi, ìbáà ṣe ènìyàn tàbí ẹranko.”

3. Nígbà náà ni Mósè sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ rántí ọjọ́ òní, ọjọ́ ti ẹ jáde kúrò ni ilẹ́ Éjíbítì, kúrò ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin ti ń ṣe ẹrú, nítorí Olúwa mú un yín jáde kúrò ni inú rẹ̀ pẹ̀lú ọwọ́ agbára. Ẹ má se jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú.

4. Òní, ní oṣù Ábíbù (oṣù kẹta ọdún tiwa) lónìí ẹ̀yin ń jáde kúrò ní Éjíbítì.

5. Ní ìgbà tí Ọlọ́run mú un yín jáde wá sí ilẹ̀ ẹ Kénánì, Hítì, Ámórì, Hífì àti ilẹ̀ àwọn Jébúsì; ilẹ̀ tí ó ti ṣe ìlérí láti fi fún àwọn baba ńlá yín, ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti oyin, ẹ ni láti pa ìsìn yìí mọ́ ní oṣù yìí.

6. Fún ọjọ́ méje ni ìwọ yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà nínú àti pé ní ọjọ́ keje ni àjọ yóò wà fún Olúwa.

Ka pipe ipin Ékísódù 13