Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 4:35-38 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

35. A fi gbogbo nǹkan wọ̀nyí hàn yín kí ẹ bá a lè gbà pé Olúwa ni Ọlọ́run. Kò sì sí ẹlòmíràn lẹ́yìn rẹ̀.

36. Ó jẹ́ kí ẹ gbọ́ ohùn rẹ̀ láti ọ̀run wá, láti kọ́ ọ yín. Ní aye, ó fi iná ńlá rẹ̀ hàn yín, ẹ sì gbọ́ ohùn rẹ̀ láti àárin iná wá,

37. torí pé ó fẹ́ràn àwọn baba ńlá yín, ó sì yan àwọn ọmọ wọn ní ipò lẹ́yìn wọn. Nípa ìwà láàyè àti nípa agbára ńlá rẹ̀ ni ó fi mú un yín kúrò ní Éjíbítì.

38. Láti lé àwọn orílẹ̀ èdè tí ó tóbi tí ó sì lágbára níwájú yín; láti le è mú un yín wá sí ilẹ̀ wọn kí ẹ lè jogún rẹ̀ bí ó ti rí lónìí.

Ka pipe ipin Deutarónómì 4