Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 4:11-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ẹ̀yin súnmọ́ tòsí ẹ sì dúró ní ẹṣẹ̀ òkè náà, nígbà tí òkè náà yọná lala lọ sókè ọrun pẹ̀lú ìkúùkù ńlá, àti òkùnkùn biribiri.

12. Olúwa sì bá yín sọ̀rọ̀ láti àárin iná náà wá. Ẹ gbọ́ àwọn ìró ohùn, ṣùgbọ́n ẹ kò rí ẹnikẹ́ni, ohùn nìkan ni ẹ gbọ́.

13. Ó sọ àwọn májẹ̀mú rẹ̀ fún un yín àní àwọn òfin mẹ́wẹ̀ẹ̀wá tí ó pàṣẹ fún un yín láti máa tẹ̀lé, ó sì kọ wọ́n sórí sílétì òkúta méjì.

14. Olúwa sọ fún mi nígbà tí ẹ gbọdọ̀ tẹ̀lée, nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ ìní yín lẹ́yìn tí ẹ bá la Jọ́dánì kọjá.

15. Ẹ kíyèsára gidigidi, torí pé, ẹ kò rí ìrísí ohunkóhun ní ọjọ́ tí Olúwa bá yín sọ̀rọ̀ ní Hórébù láti àárin iná wá. Torí náà ẹ sọ́ra yín gidigidi,

16. kí ẹ ma ba à ba ara yín jẹ́ nípa ṣíṣe ère fún ara yín, àní ère lóríṣìíríṣìí yálà èyí tí ó ní ìrísí ọkùnrin tàbí tí obìnrin,

17. tàbí ti ẹranko orí ilẹ̀, tàbí ti ẹyẹ tí ń fò lófuurufú,

Ka pipe ipin Deutarónómì 4