Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 32:34-40 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

34. “Èmi kò to èyí jọ ní ìpamọ́èmi kò sì fi èdìdì dìí ní ìṣúra à mi?

35. Ti èmi ni láti gbẹ̀san; Èmi yóò san án fún wọnní àkókò tí ẹ̀sẹ̀ wọn yóò yọ;ọjọ́ ìdàmú wọn sún mọ́ etíléohun tí ó sì ń bọ̀ wá bá wọn yára bọ̀.”

36. Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn an rẹ̀yóò sì ṣàánú fún àwọn ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀nígbà tí ó bá rí i pé agbára wọn lọ tántí kò sì sí ẹnìkan tí ó kù, ẹrú tàbí ọmọ.

37. Yóò wí pé: “Òrìṣà a wọn dà báyìí,àpáta tí wọ́n fi ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé e wọn,

38. ọlọ́run tí ó jẹ ara ẹbọ wọntí ó ti mu ọtí i wáìnì ẹbọ ohun mímu wọn?Jẹ́ kí wọn dìde láti gbà wọ́n!Jẹ́ kí wọn ṣe ààbò fún un yín!

39. “Wòó báyìí pé: èmi fúnra à mi, èmi ni!Kò sí ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi.Mo sọ di kíkú mo sì tún sọ di ààyè,mo ti ṣá lọ́gbẹ́ Èmi yóò sì mu jiná,kò sí ẹni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ ọ̀ mi.

40. Mo gbé ọwọ́ mi sókè ọ̀run mo sì wí pé:Èmi ti wà láàyè títí láé,

Ka pipe ipin Deutarónómì 32