Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 31:3-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Olúwa Ọlọ́run rẹ fúnra rẹ̀ ni yóò rékọjá fún ọ. Yóò pa àwọn orílẹ̀ èdè yìí run níwájú ù rẹ, ìwọ yóò sì mú ìní ilẹ̀ wọn, Jósúà náà yóò rékọjá fún ọ, bí Olúwa ti sọ.

4. Olúwa yóò sì ṣe fún wọn ohun tí ó ti ṣe sí Ṣíhónì àti sí Ógù ọba Ámórì, tí ó parun pẹ̀lú ilẹ̀ ẹ wọn.

5. Olúwa yóò fi wọ́n fún ọ, kí o sì ṣe sí wọn gbogbo èyí tí mo ti pa láṣẹ fún ọ.

6. Jẹ́ alágbára kí o sì ní ìgboyà. Má se bẹ̀rù tàbí jáyà nítorí i wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń lọ pẹ̀lú ù rẹ; Òun kò ní fi ọ́ sílẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”

7. Nígbà náà ni Mósè pe Jóṣúà ó sì wí fún un níwájú gbogbo Ísírẹ́lì pé, “Jẹ́ alágbára àti onígboyà, nítorí o ní láti lọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn wọ̀nyí sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fún wọn, kí o sì pín ilẹ̀ náà láàrin wọn bí ogún wọn.

8. Olúwa fúnra rẹ̀ ń lọ níwájú rẹ yóò sì wà pẹ̀lú ù rẹ; kò ní fi ọ́ sìlẹ̀ tàbí kọ̀ ọ́ sìlẹ̀. Má ṣe bẹ̀rù má sì ṣe fòyà.”

9. Nígbà náà ni Móṣè kọ òfin yìí kalẹ̀ ó sì fi fún àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Léfì, tí ń gbé àpótí i májẹ̀mú Olúwa, àti fún gbogbo àwọn àgbà ní Ísírẹ́lì.

Ka pipe ipin Deutarónómì 31