Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 3:20-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. títí di ìgbà tí Olúwa yóò fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi bí ó ti fún un yín, àti ìgbà tí àwọn náà yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún wọn ní ìhà kejì Jọ́dánì. Nígbà náà ni ọ̀kọ̀ọ̀kan yín tó lè padà lọ sí ìní rẹ̀ tí mo fún un.”

21. Nígbà náà ni mo pàṣẹ fún Jósúà pé, “Ìwọ tí fi ojú rẹ rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ṣe sí àwọn ọba méjèèjì wọ̀nyí. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò ṣe sí àwọn ilẹ̀ ọba tí ẹ̀yin n lọ.

22. Ẹ má ṣe bẹ̀rù wọn, Olúwa Ọlọ́run yín tìkálára rẹ̀ ni yóò jà fún un yín.”

23. Nígbà náà ni mo bẹ Olúwa wí pé,

Ka pipe ipin Deutarónómì 3