Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 28:62-68 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

62. Ìwọ tí ó dàbí àìmòye bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run yóò sẹ́ku kékeré níye, nítorí tí o kò ṣe ìgbọràn sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.

63. Gẹ́gẹ́ bí ó ti dùn mọ́ Olúwa nínú láti mú ọ ṣe rere àti láti pọ̀ si ní iye, bẹ́ẹ̀ ni yóò dùn mọ́ ọ nínú láti bì ọ́ ṣubú kí ó sì pa ọ́ run. Ìwọ yóò di fífà tu kúrò lórí ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.

64. Nígbà náà ni Olúwa yóò fọ́n ọ ká láàrin gbogbo orílẹ̀ èdè, láti òpin kan ní ayé sí òmíràn. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò ti sin ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run igi àti ti òkúta. Èyí tí ìwọ àti àwọn baba rẹ kò mọ̀.

65. Ìwọ kì yóò sinmi láàrin àwọn orílẹ̀ èdè náà, kò sí ibi ìsinmi fún àtẹ́lẹ́ṣẹ̀ rẹ. Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti fún ọ ní ọkàn ìnàngà, àárẹ̀ ojú, àti àìnírètí àyà.

66. Ìwọ yóò gbé ní ìdádúró ṣinṣin, kún fún ìbẹ̀rù-bojo lọ́sàn án àti lóru, bẹ́ẹ̀ kọ́ láé ni ìwọ yóò rí i ní àrídájú wíwà láyé rẹ.

67. Ìwọ yóò wí ní òwúrọ̀ pé, “Bí ó tilẹ̀ lè jẹ́ pé ìrọ̀lẹ́ níkan ni!” nítorí ẹ̀rù tí yóò gba ọkàn rẹ àti ìran tí ojú rẹ yóò máa rí.

68. Olúwa yóò rán ọ padà nínú ọkọ̀ sí Éjíbítì sí ìrìnàjò tí mo ní ìwọ kì yóò lọ mọ́. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò tún fi ara rẹ fún àwọn ọ̀ta à rẹ gẹ́gẹ́ bí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò rà ọ́.

Ka pipe ipin Deutarónómì 28