Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 2:33-37 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. Olúwa Ọlọ́run wa fi lé wa lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ ni a ṣẹ́gun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo ológun rẹ̀.

34. Nígbà náà, gbogbo ìlú wọn ni a kó tí a sì pa wọ́n run pátapáta tọkùnrin, tobìnrin àti gbogbo ọmọ wọn. A kò sì dá ẹnikẹ́ni sí.

35. Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú tí a ṣẹ́gun fún ara wa.

36. Láti Áróérì, létí odò Ánónì àti láti àwọn ìlú tí ó wà lẹ́bàá odò náà títí ó fi dé Gílíádì, kò sí ìlú tí ó lágbára jù fún wa, Olúwa Ọlọ́run wa fi gbogbo wọn fún wa.

37. Ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa Ọlọ́run wa, ẹ kò súnmọ́ ọ̀kan nínú ilẹ̀ àwọn ará Ámónì, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò dé ilẹ̀ tí ó lọ sí Jábókù, tàbí ilẹ̀ tí ó yí àwọn ìlú òkè e nì ká.

Ka pipe ipin Deutarónómì 2