Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 2:28-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. Ẹ ta oúnjẹ tí a ó jẹ àti omi tí a ó mu fún wa ní iye owó wọn. Kìkì kí ẹ sáà jẹ́ kí a rìn kọjá:

29. gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Éṣáù tí ó ń gbé ní Séírì àti àwọn ará Móábù tí ó ń gbé ní Árì, ti gbà wá láàyè títí a fi la Jọ́dánì já dé ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò fún wa.”

30. Ṣùgbọ́n Ṣíhónì ọba Héṣíbónì kò gbà fún wa láti kọjá. Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti mú ọkàn rẹ̀ yigbì, àyà rẹ̀ sì kún fún agídí kí ó ba à le fi lé e yín lọ́wọ́, bí ó ti ṣe báyìí.

31. Olúwa sì bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kíyèsí i, mo ti bẹ̀rẹ̀ sí ní fi Síhónì àti ilẹ̀ rẹ̀ lé e yín lọ́wọ́. Báyìí, ẹ máa ṣẹ́gun rẹ̀, kí ẹ sì gba ilẹ̀ rẹ̀.”

32. Nígbà tí Síhónì àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ̀ jáde wá láti bá wa jagun ní Jáhásì,

Ka pipe ipin Deutarónómì 2