Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Deutarónómì 16:17-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Olúkúlùkù u yín gbọdọ̀ mú ẹ̀bùn wá bí Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún fún un tó.

18. Ẹ yan àwọn adájọ́ àti àwọn olóyè fún ẹ̀yà a yín kọ̀ọ̀kan, ní gbogbo ìlú tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, wọ́n sì gbọdọ̀ máa fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn.

19. Ẹ má ṣe yí ẹjọ́ po, ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe ojúṣàájú. Ẹ má ṣe gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọgbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ òdodo jẹ́.

20. Ẹ tẹ̀lé ìdájọ́ òtítọ́ àní ìdájọ́ òtítọ́ nìkan, kí ẹ báà lè gbé kí ẹ sì gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín ń fún un yín.

21. Ẹ má ṣe ri òpó òrìṣà áṣérà ṣẹ́gbẹ̀ẹ́ pẹpẹ tí ẹ ti mọ fún Olúwa Ọlọ́run yín.

22. Ẹ kò gbọdọ̀ gbé òkúta òrìṣà gbígbẹ́ kan kalẹ̀ fún ara yín, nítorí èyí ni Olúwa Ọlọ́run yín kórìíra.

Ka pipe ipin Deutarónómì 16